Moshood Káṣìmawòó Ọláwálé Abíọ́lá (August 24, 1937 - July 7, 1998) tí ó túmọ̀ sí M.K.O Abíọ́lá jẹ́ ọmọ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà.
A bi ní ìlú Abẹ́òkúta ní Ìpínlẹ̀ Ògùn. Ó jẹ́ oníṣòẁò,òǹtẹ̀wé, olóṣèlú àti olóyè ilẹ̀ Yorùbá Ẹ̀gbá pàtàpátá. Ó díje sípò Ààrẹ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ní ọdún 1993, òun náà sì ni gbogbo ènìyàn gbàgbọ́ tí wọ́n sì fẹnukò sí jákè-jádò orílẹ-èdè Nàìjíríà wípé ó jáwé olúborí nígbà tí olóri ìjọba ológun ìgbà náà Ibrahim Babangida kò kéde rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olúborí ètò ìdìbò náà tí ó sì fi ẹ̀sùn àìṣòtítọ́ àti àìṣòdodo ètò ìdìbò yàn náà. M.K.O kú ní ọdún 1998.
Moshood Abiola | |
---|---|
Ọjọ́ìbí | Abeokuta | 24 Oṣù Kẹjọ 1937
Aláìsí | 7 July 1998 Abuja | (ọmọ ọdún 60)
Orílẹ̀-èdè | Nàìjíríà |
Orúkọ míràn | M.K.O Ab́iọ́lạ́ |
Iṣẹ́ | Okowo, Oloselu, Oluranilowo. |
Gbajúmọ̀ fún | Being arrested following a Presidential election in Nigeria which he won/Philanthropy |
Olólùfẹ́ | Simbiat Atinuke Shoaga Kudirat Olayinka Adeyemi Adebisi Olawunmi Oshin Doyinsola Abiola Aboaba Modupe Onitiri-Abiola Remi Abiola (+other women) |
Àwọn ọmọ | Abdulateef Kola Abiola Dupsy Abiola Hafsat Abiola Rinsola Abiola Khafila Abiola (+other children) |
Moshood Abíọ́lá ni àkọ́bí bàbá àti ìyá rẹ̀ lẹ́yìn ìkúnlẹ̀ ọmọ kẹtàlélógún, ìdí èyí ní ó fàá tí wọ́n fi dúró títí di ẹ̀yìn ọdún mẹ́ẹ̀dógún (15 years) kí àwọn òbí rẹ̀ tó fún lórúkọ rẹ̀ “Kasimawo” . Moshood fakọyọ nínú ìmọ̀ ìdágbálé (entrepreneur) láti ìgb̀a èwe rẹ̀, ó bẹ̀rè iṣẹ́ igi-ṣíṣẹ́ tà láti ọmọ ọdún mẹ́sàán. Ó ma ń jí ní ìdájí lọ sóko igi láti wági tí yóò tà ṣáájú kí ó tó lọ sị́ ilé-ìwé kí òun àti bàbá rẹ̀ tó ti rúgbo pẹ̀lú àwọn àbúrò rẹ̀ kó lè rówó ná. Nígb̀a tí ó t́o ọmọ ọdún mẹ́ẹ̀dógún (15 years), ó dá ẹgbẹ́ eré kan kalẹ̀ tí wọ́n ma ń kọrin kiri láti lè rí óúnjẹ jẹ níbi ìnáwo èyíkéyìí tí wọ́n bá lọ. Láìpẹ́, ó di gbajú-gbajà níbi orin rẹ̀ tó ń kó kiri, ó sì di ẹni tí ó ń bèrè fún owó iṣẹ́ kí wọ́n tó kọrin lóde ìnáwó kòkan. Àwọn owó tí ó ń rí níbi eré rẹ̀ yìí nị́ ó fi ń ran ẹbí rẹ̀ lọ́wọ́ tí ó sì ń san owó ilé-ẹ̀kọ́ gíga tí ìjọ Onítẹ̀bọmi tí ó wà ní Abéòkúta . Abíọ́́lá jẹ́ Olóòtú ìwé ìròyìn ọ̀sọ̀ọ̀sẹ̀ ilé-ìwé wọn tí ó ń jẹ́ The Trumpeter tí Olúṣẹ́gun Ọbásanjọ́ sì jẹ́ igbákejì rẹ. Ó dára pọ̀ mọ́ ẹgbẹ́ National Council of Nigeria and the Cameroons ní ìgbà tí ó di ọmọ ọdún mọ́kàndínlógún nítorí ìfẹ́ tí ó ní sí ètò òṣèlú àwa arawa lábẹ́ àsíá Ọbáfẹ́mi Awólọ́wọ̀ olùdásílẹ̀ ẹgbẹ́ òṣèlú Action Group.
Ni odun 1960, Moshood gba sikolashipu ijọba lati ka iwe ni University ti Glasgow ni ilu Scotland ni bii ti o gba oye ni isiro sebe sebe o o je oye oniṣiro iwiregbe. Moshood di Ẹlẹgbẹ ti Institute of Chartered Accountants of Nigeria (ICAN) (ICAN).
This article uses material from the Wikipedia Yorùbá article M. K. O. Abíọ́lá, which is released under the Creative Commons Attribution-ShareAlike 3.0 license ("CC BY-SA 3.0"); additional terms may apply (view authors). Gbogbo ohun inú ibí yìí wà lábẹ́ CC BY-SA 4.0 àyàfi tí a bá sọ pé kò rí bẹ̀ẹ̀. Images, videos and audio are available under their respective licenses.
®Wikipedia is a registered trademark of the Wiki Foundation, Inc. Wiki Yorùbá (DUHOCTRUNGQUOC.VN) is an independent company and has no affiliation with Wiki Foundation.