Folasade Ogunsola

Folashade Tolúlọpẹ́ Ògúnṣọlá ẹni tí wọ́n bí ní ọdún 1958 jẹ́ ọ̀jọ̀gbọ́n nínú ìmọ̀ Medical Microbiology, òun sì ni Alákòóso àgbà fún ilé-ẹ̀kọ́ Yunifásítì ìlú Èkó lásìkò tí a ń kọ àpilẹ̀kọ yí.

Ó jẹ́ onímọ̀ nípa bí a ń kojú àrùn pàá pàá jùlọ kòkòrò àrùnHIV/AIDs. Ògúnṣọla ti kọ́kọ́ di ipò Alákòóso agbà (Provosti) ti ilé-ẹ̀kọ́ imọ̀ ìṣègùn oyinbo ti (College of Medicine) ti Yunifásitì ìlú Eko mú rí, òun sì ni obìnrin akọ́kọ́ tí o kọ́kó di ipò náà mú. Ó tún wà lára àwọn ígbákejì adarí ti Yunifásitì náà, ipò ti o di mú láàrín ọdún 2017 sí ọdún 2021. A fi si adilemu ipò adari Yunifásitì ìpínlè Èkó ni ojo kerinlelogun osu Kejo(24 August) odun 2020) léyìn igba ti won yo Òjògbón Oluwatoyin Ogundipe ni ipò adari ilé-ìwé náà. Ni ojo keje osu kewa(7 Oct 2022), a yan Ogunshola gégé bi adari ilé-ìwé náà, oun si ni obinrin àkókó ti o di ipò náà mu.

Folasade Ogunsola
Adarí kẹtàlá Yunifásitì ìlú Èkó
Lọ́wọ́lọ́wọ́
Ó gun orí àga
12 November 2022
AsíwájúOluwatoyin Ogundipe
Deputy Vice Chancellor (Development Services), University of Lagos
In office
2017–2021
Àwọn àlàyé onítòhún
Ọjọ́ìbí
Folasade Tolulope Mabogunje

1958 (ọmọ ọdún 65–66)
Ọmọorílẹ̀-èdèNigerian
Alma materCollege of Medicine, Unilag
(Masters in Medical microbiology)
College of Medicine, University of Wales, Cardiff
(Doctor of Philosophy in Medical microbiology)

Ìbẹ̀rẹ̀ ayé àti ẹ̀kọ́ rẹ̀

Wọ́n tọ́ Ògúnṣọlá dàgbà nínú ilé-ẹ̀kọ́ Yunifásitì ìlú Ibadan níbi tí bàbá rè, Akin Maábògùnjẹ́ ti jẹ́ olùkọ́. Nígba ti ó wà ni omodé, o ma ń ṣe bi àwọn onímò òyìnbó pẹ́lú bí ó ṣe ma ń fi àwọn bèbí ìṣeré ọmọdé ṣeré, tí ó sì ma ń ṣe bí ẹni wípé òun ń ṣe itọ́jú wọn.

Ó lo ilé-ìwé Queen's College, ìpinlè Èkó. Ni arin odún 1974 si odun 1982, o gbà àmì-èye àkókó rè ni Yunifásitì ìlú Ifè ati àmì-èye Master degree rè ní College of Medicine ti yunifásitì ìlú Eko, o si tún tesiwaju láti gba àmì-èye doctorate rè ni Yunifásitì ìlú Wales larin odun 1992 si 1997.

Isé rè

A yan Ogunshola láti se adilemu ipò adari yunifásitì ìpinlè Eko fun ìgbà dí è ni odun 2020 nígbà ti wahala be sile ni ilé-ìwé náà nitori pé awon alaga ilé-ìwé náà yo adari rè. Ó tun wa lára awon ígbákejì adari ilé-ìwé náà, ki o to di pé o di adilemu ipo adari rè.. Kí ó tó dé ipò òkan lara àwon ígbákejì adari ilé-ìwé náà, óun ni provosti ilé-ìwé ìmò òyìnbó(College of Medicine).

Awon iwádí re wa lori bi a ti ún koju àwon àárun ti Virusi fa. Oun ni oludari awadi àjo AIDS Prevention Initiative in Nigeria(APIN) ni Yunifásitì ìlú Eko, oun tun ni alaga àjo Infection Control Committee ti Teaching Hospital ìpinlè Eko(LUTH). Ogunshola tun jé alaga National Association of Colleges of Medicine in Nigeria.

Ni odun 2018, o soro lori ero rè nípa kíkojú aarun ni Nàìjíríà. O ni aini imototo àti ilo ogun Antibiotics ju botiye lo wa lara idi ti ògùn apa àárun o fi ka àwon kokoro to un fa aàrùn mó. O wà lara omo egbé àkókò ti egbé Nigerian Society for Infection control ní odun 1998 o si wa lara àwon omo egbé Global Infection Prevention and Control Network.

Àwon ìwé àti àtèjáde rè

  • Modification of a PCR Ribotyping Method for Application as a Routine Typing Scheme for Clostridium difficile, 1996
  • Infections caused by Acinetobacter species and their susceptibility to 14 antibiotics in Lagos University Teaching Hospital, Lagos, 2002
  • Attitudes of Health Care Providers to Persons Living with HIV/AIDS in Lagos State, Nigeria, 2003
  • Extended-Spectrum β-Lactamase Enzymes in Clinical Isolates of Enterobacter Species from Lagos, Nigeria, 2003
  • Risk factors for ectopic pregnancy in Lagos, Nigeria, 2005
  • Challenges for the sexual health and social acceptance of men who have sex with men in Nigeria, 2007
  • Associated risk factors and pulsed field gel electrophoresis of nasal isolates of Staphylococcus aureus from medical students in a tertiary hospital in Lagos, Nigeria, 2007
  • Effectiveness of cellulose sulfate vaginal gel for the prevention of HIV infection: results of a Phase III trial in Nigeria, 2008
  • The effects of antimicrobial therapy on bacterial vaginosis in non‐pregnant women, 2009
  • Antimicrobial susceptibility and serovars of Salmonella from chickens and humans in Ibadan, Nigeria, 2010
  • Characterization of methicillin-susceptible and -resistant staphylococci in the clinical setting: a multi-centre study in Nigeria, 2012
  • A community-engaged infection prevention and control approach to Ebola, 2015

Àwon Ìtókasí

Tags:

Folasade Ogunsola Ìbẹ̀rẹ̀ ayé àti ẹ̀kọ́ rẹ̀Folasade Ogunsola Isé rèFolasade Ogunsola Àwon ìwé àti àtèjáde rèFolasade Ogunsola Àwon ÌtókasíFolasade OgunsolaObìnrinYunifásítì ìlú ÈkóÀrùn

🔥 Trending searches on Wiki Yorùbá:

San Jose, Kalifọ́rníà8 MayRichard Mofe DamijoSyngman RheeCharles J. PedersenFiennaNọ́mbà átọ̀mùStephen HarperAisha AbdulraheemPeter O'Toole.bgRamesses VIIOrílẹ̀ èdè AmericaÌṣíròTurkeyIgbesi aye mi ninu igbo ti Awọn ẹmi (aramada)(6065) 1987 OC29 AugustISO 8601John LewisNarendra ModiẸ̀sìn KrístìÈṣùCaliforniaGeorge Clinton (Igbákejì Ààrẹ)Gírámà Yorùbá(9981) 1995 BS3ISO 10487Àwọn Ìdíje Òlímpíkì Ìgbà Oru 2004Tuedon Morgan5 AugustTegucigalpaWashington, D.C.Oba Saheed Ademola ElegushiAuguste BeernaertZambiaFacebook31 JulyAyò ọlọ́pọ́n20634 MarichardsonÌwé Àṣẹ Aṣàlàyé Ọ̀fẹ́ GNUAgbègbè Ìjọba Ìbílẹ̀ IkoleÀdánidáKàlẹ́ndà Gregory1229 Tilia773 IrmintraudMichigan.jp2437 AmnestiaChinedu IkediezeOrin apalaEhoroBadagryMary AkorBhumibol AdulyadejXGbogbo Ìpawó Orílẹ̀-èdè234 BarbaraGeorge Walker BushYttrium13 AugustPeter Fatomilola🡆 More