Babatunde Omidina tí orúkọ ìnagijẹ rẹ̀ ń jẹ́
Babatunde Omidina | |
---|---|
Ọjọ́ìbí | Lagos Island | 22 Oṣù Kẹjọ 1958
Aláìsí | oṣù Belu (Nòfẹ́mbà) ọdún un 2021 |
Orílẹ̀-èdè | Nigerian |
Orúkọ míràn | Baba Suwe |
Ọmọ orílẹ̀-èdè | Nigerian |
Iṣẹ́ |
|
Ìgbà iṣẹ́ | 1972- 2021 |
Notable work | Aṣọ Ìbora |
Bàba Sùwé (tí wọ́n bí ní Ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kẹjọ ọdún 1958 jẹ́ gbajúgbajà òṣèré sinimá àgbéléwò ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà. Ó jẹ́ òṣèré aláwàdà, ipa àwàdà ni ó sìn máa ń kó nínú sinimá tàbí eré orí ìtàgé tí ó bá ti kópa. Eré orí ẹ̀rọ tẹlifíṣọ̀n kan tí àkọ́lé rẹ̀ ń jẹ́ "Ẹ̀rín Kèékèé" ni ìràwọ̀ rẹ̀ tí bú jáde, nínú eré yìí ni orúkọ ìnagijẹ rẹ̀ yìí tí jẹyọ. Ọjọ́ kejìlélógún, oṣù Belu (Nòfẹ́mbà) ọdún un 2021 ni Bàbá Sùwé dágbére fáyé.
Babatunde Omidina bẹ̀rẹ̀ eré tíátà lọ́dún 1971. O di ìlúmọ̀ọ́kà nínú eré orí ẹ̀rọ tẹlifíṣọ̀n kan tí àkọ́lé rẹ̀ ń jẹ́ "Ẹ̀rín Kèékèé". Kódà, nínú eré aláwàdà yìí ni ó ti gba orúkọ ìnagijẹ rẹ̀, Bàba Sùwé. Lẹ́yìn èyí, ìràwọ̀ rẹ̀ tún búyọ sì í nígbà tí ó kópa nínú àwọn sinimá-àgbéléwò lóríṣiríṣi.
This article uses material from the Wikipedia Yorùbá article Babatunde Omidina, which is released under the Creative Commons Attribution-ShareAlike 3.0 license ("CC BY-SA 3.0"); additional terms may apply (view authors). Gbogbo ohun inú ibí yìí wà lábẹ́ CC BY-SA 4.0 àyàfi tí a bá sọ pé kò rí bẹ̀ẹ̀. Images, videos and audio are available under their respective licenses.
®Wikipedia is a registered trademark of the Wiki Foundation, Inc. Wiki Yorùbá (DUHOCTRUNGQUOC.VN) is an independent company and has no affiliation with Wiki Foundation.