Aisha Yesufu: Ajafeto omo ènìyàn ni orílè-èdè Nàìjirià

Aisha Yusufu (tí a bí ní ọjọ́ kejìlá oṣù kejìlá ọdún 1973 ní Ipinle Kano) jẹ́ ajàfẹ́tọ̀ ọ́ ọmọ ènìyàn, ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà àti alábàṣiṣẹ́pọ̀ ẹgbẹ́ tí ó ń polongo fún ìdápadà àwọn ọmọ obìnrin wa (Bring Back Our Girls Movement), èyí tí í ṣe ẹgbẹ́ alágbàwí tí ó ń pe Ìjọba sí àkíyèsi lórí í àwọn ọmọbìnrin tí ó lé ní igba láti ilé-ẹ̀kọ́ sẹ́kọ́ńdìrì ti Chibok ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà tí àwọn ẹgbẹ́ oníjàgídíjàgan Boko Haram jí gbé ní ọjọ́ kẹrìnlá oṣù kẹrin ọdún 2014.

Yesufu wà lára àwọn obìnrin tí wọ́n ń fi ẹ̀rónú hàn ní ilé Ìgbìmọ̀ Aṣòfin ti orílẹ̀-èdè Nàìjíríà, èyí tí ó wà ní Abuja, Olú-ìlú Nàìjíríà, ní ọgbọ̀n ọjọ́ oṣù kẹrin, ọdún 2014.

Aisha Yesufu
Aisha Yesufu: Ajafeto omo ènìyàn ni orílè-èdè Nàìjirià
Aisha Yesufu leading the EndSARS Protest in Abuja, on October 10, 2020.
Ọjọ́ìbíAisha Yesufu
Oṣù Kejìlá 12, 1973 (1973-12-12) (ọmọ ọdún 50)
Kano State
Orílẹ̀-èdèNàìjíríà
Iléẹ̀kọ́ gígaBayero University Kano
Iṣẹ́Socio-political activist, microbiologist, businesswoman
Gbajúmọ̀ fúnBring Back Our Girls, End SARS
Àwọn ọmọ2

Yesufu tún wà lára àwọn tí ó léwájú nígbà tí àwọn ọ̀dọ́ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ń pè fún fífòpin sí SARS (END SARS), èyí tí ó ń pe àkíyèsi si àṣejù tí ẹ̀yà kan nínú iṣé ọlọ́pàá orílẹ̀-èdè Nàìjíríà tí wọ́n ń pè ní Special Anti Robery Squad (SARS) ń ṣe. Yesufu sọ wípé òun kò ní fi ìjà kíkéde ìfòpin sí àwọn ọlọ́pàá SARS ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà sílẹ̀ fún àwọn ọmọ òun.

Ìbẹ̀rẹ̀ ayé rẹ

Ipinle Kano, níbi tí wọ́n bí Yesufu sí ná à ni wọ́n tí tọ ọ dàgbà. Yesufu ní ìrírí lórí i ìṣòro tí ó wà nínú n kí ènìyàn jẹ́ ọmọbìnrin ní àyíká tí kò fibẹ́rẹ̀ sí ìmọ̀ ẹ̀kọ́. Nínú ọ̀rọ̀ rẹ tí ó sọ, ó wípé "Nígbà tí mo wà ní ọmọ ọdún mọ́kànlá, ń kò ní àwọn ọmọbìnrin kankan ní ọ̀rẹ́ nítorí pé gbogbo wọn ni wọ́n ti gbé níyàwó, ṣùgbọ́n nítorí mo fẹ́ ní ìmọ̀ ẹ̀kọ́ ni mo ṣe kúrò ní agbègbè tí kò lajú." Aisha Yusufu tún sọ wípé ọ̀pọ̀lọpọ̀ nínú àwọn ọmọ tí àwọn ẹlẹgbẹ́ òun bí ti fẹ́rẹ̀ tún má a bí ọmọ nígbàtí òun ṣe ìgbéyàwó ní ọmọ ọdún mẹ́rìnlélógún.

Ìgbésí ayé rẹ

Yesufu àti ọkọ rẹ̀ tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Aliu, ẹni tí ó ṣe ìgbéyàwó pẹ̀lú rẹ ní ọdún 1966, ni wọ́n bí ọmọ méjì tí orúkọ wọn ń jẹ́ Amir àti Aliyah.

Awọn itọkasi

Tags:

Boko HaramIpinle KanoNàìjíríà

🔥 Trending searches on Wiki Yorùbá:

5 AprilGírámà YorùbáSenior Advocate of NigeriaBíbélì Mímọ́29 FebruaryÀjákálẹ̀ àrùn káàkiriayé èrànkòrónà ọdún 2019 2020AṣọÌṣúpọ̀ olùgbéÈkó1 August28 JulyÀwọn Ìdíje Òlímpíkì Ìgbà Oru 1936Ethiopia27 DecemberAustralopithecinesÌṣọ̀kan ÁfríkàMọfọ́lọ́jì èdè YorùbáRauf AregbesolaÀgùàlàÌjà fẹ́tọ̀ọ́ ObìnrinShepseskafMassachusetts8 AprilWikiAlaskaDubai6 JulyÀwọn Ẹ́mírétì Árábù Aṣọ̀kanWeb browserTalcUlf von EulerÀwọn Ìdíje Òlímpíkì Ìgbà Oru 1956New ZealandOṣù KẹrinÌjíptìÁsíàÌbàdàn.nzÈdè ÀmháríkìJean-Paul SartreÀwọn Erékùṣù Marshall1214 RichildeỌ́ksíjìnJack PalanceÈdè EsperantoPierre NkurunzizaNàìjíríà12 JuneOrin WéréGúúsù ÁfríkàOwóBèbè Ìlàòrùn1 Oṣù Kínní2024Victoria University of ManchesterPonun StelinMauritaniaItálíàỌ̀rọ̀ayéijọ́unHassan RouhaniPolinésíà FránsìOrílẹ̀-èdè PalẹstínìOjúewé Àkọ́kọ́Fúnmiláyọ̀ Ransome-KútìKonrad AdenauerAlákànIsaac Newton13 DecemberFriedrich EngelsÈdè Ítálì🡆 More